Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 25:13-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Òun àti irú ọmọ rẹ̀ yóò ní májẹ̀mú láéláé fún iṣẹ́ àlùfáà, nítorí pé ó ní ìtara fún Ọlọ́run rẹ̀ láti fi yẹ́ Ọlọ́run sí, ó sì ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.”

14. Orúkọ ọmọ Ísírẹ́lì tí a pa pẹ̀lú obìnrin Mídíánì náà ni Símírì, ọmọ Ṣálù, olórí ilé kan nínú àwọn ọmọ Símónì.

15. Orúkọ ọmọbìnrin Mídíánì náà tí a pa ni Kósíbì ọmọbìnrin Súrù, tí ṣe olóyè àwọn ẹ̀yà kan nínú ìdílé kan ní Mídíanì.

16. Olúwa sì tún sọ fún Mósè pé,

17. “Ka àwọn ará Mídíánì sí ọ̀ta, kí o sì pa wọ́n,

18. nítorí pé wọ́n ṣe sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀ta nígbà tí wọ́n tàn yín nípa ìṣẹ̀lẹ̀ Péórì, àti arábìnrin wọn Kósíbì ọmọbìnrin ìjòyè Mídíánì kan, obìnrin tí a pa nígbà tí àjàkálẹ̀-àrùn ṣẹlẹ̀ nítorí Péórì.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 25