1. Olúwa sọ fún Mósè pé,
2. “Rán ènìyàn díẹ̀ láti lọ yẹ ilẹ̀ Kénánì wò èyí tí mo ti fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì. Rán ẹnìkọ̀ọ̀kan, tí ó jẹ́ olórí láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.”
3. Mósè sì rán wọn jáde láti Aginjù Páránì gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa. Gbogbo wọn jẹ́ olórí àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì.
4. Orúkọ wọn nìwọ̀nyí:láti inú ẹ̀yà Rúbẹ́nì Ṣámuá ọmọ Ṣákúrì;
5. láti inú ẹ̀yà Símónì, Ṣáfátì ọmọ Hórì;
6. láti inú ẹ̀yà Júdà, Kélẹ́bù ọmọ Jéfúnè;
7. Láti inú ẹ̀yà Ísíkárì, Ígálì ọmọ Jósẹ́fù;
8. Láti inú ẹ̀yà Éfúráímù, Ósíà ọmọ Núnì;