1. Olúwa sọ fún Mósè pé,
2. “Rán ènìyàn díẹ̀ láti lọ yẹ ilẹ̀ Kénánì wò èyí tí mo ti fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì. Rán ẹnìkọ̀ọ̀kan, tí ó jẹ́ olórí láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.”
3. Mósè sì rán wọn jáde láti Aginjù Páránì gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa. Gbogbo wọn jẹ́ olórí àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì.