Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nehemáyà 4:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà tí Ṣáńbálátì gbọ́ pé àwa ń tún odi náà mọ, ó bínú, ó sì bínú púpọ̀. Ó fi àwọn ará Júù ṣe ẹlẹ́yà,

2. ó sọ níwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti níwájú àwọn ọmọ ogun Ṣamáríà pé, “Kí ni àwọn aláìlera Júù wọ̀nyí ń ṣe yìí? Ṣé wọn yóò mú odi wọn padà ni? Ṣé wọn yóò rú ẹbọ ni? Ṣé wọn yóò paríi rẹ̀ lóòjọ́ ni bí? Ṣé wọ́n lè mú òkúta tí a ti ṣun láti inú òkítì padà bọ̀ sípò tí ó jóná bí wọ́n ṣe wà yẹn?”

3. Tóbíyà ará Ámónì, ẹni tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wí pé, “Ohun tí wọ́n ń mọ—bí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ lásán bá gùn-ún sókè, yóò fọ́ odi òkúta wọn lulẹ̀!”

Ka pipe ipin Nehemáyà 4