Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 26:29-37 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Ebi náà yóò pa yín débi pé ẹ ó máa jẹ ẹran ara àwọn ọmọ yín ọkùnrin, àti àwọn ọmọ yín obìnrin.

30. Èmi yóò wó àwọn pẹpẹ òrìṣà yín, lórí òkè níbi tí ẹ ti ń sìn: Èmi yóò sì kó òkú yín jọ, sórí àwọn òkú òrìṣà yín. Èmi ó sì kóríra yín.

31. Èmi yóò sọ àwọn ìlú yín di ahoro, èmi yóò sì ba àwọn ilé mímọ́ yín jẹ́. Inú mi kì yóò sì dùn sí òórùn ọrẹ yín mọ́.

32. Èmi yóò pa ilẹ̀ yín run débi pé ẹnu yóò ya àwọn ọ̀ta yín tí ó bá gbé ilẹ̀ náà.

33. Èmi yóò mú ogun dé bá yín: Èmi yóò sì fọ́n yín ká gbogbo àwọn ilẹ̀ àjèjì, ilẹ̀ yín yóò sì di ahoro: àwọn ìlú yín ni a ó sì parun.

34. Ilẹ̀ náà yóò ní ìsinmi (tí kò ni lákòókò ìsinmi rẹ̀) fún gbogbo ìgbà tí ẹ fi wà ní ilẹ̀ àjèjì tí ẹ kò fi lò ó. Ìlẹ̀ náà yóò sinmi láti fi dípò ọdún tí ẹ kọ̀ láti fún un.

35. Níwọ̀n ìgbà tí ẹ kò lò ó, ilẹ̀ náà yóò ní ìsinmi tí kò ní lákòókò ìsinmi rẹ̀ lákókò tí ẹ fi ń gbé orí rẹ̀.

36. “ ‘Èmi yóò jẹ́ kí ó burú fún àwọn tí ó wà ní ilẹ̀ ìgbékùn débi pé ìró ewé tí ń mì lásán yóò máa lé wọn sá. Ẹ ó máa sáré bí ìgbà tí wọ́n ń lé yín lójú ogun. Ẹ ó sì subú láìsí ọ̀ta láyìíká yín

37. Wọn yóò máa subú lu ara wọn, bí ẹni tí ń sá fún ogun nígbà tí kò sí ẹni tí ń lé yín. Ẹ̀yin kì yóò sì ní agbára láti dúró níwájú ọ̀ta yín.

Ka pipe ipin Léfítíkù 26