Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 26:28-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Ní ìbínú mi èmi yóò korò sí yín, èmi tìkara mi yóò fìyà jẹ yín ní ìgbà méje nítorí ẹ̀ṣẹ̀ yín.

29. Ebi náà yóò pa yín débi pé ẹ ó máa jẹ ẹran ara àwọn ọmọ yín ọkùnrin, àti àwọn ọmọ yín obìnrin.

30. Èmi yóò wó àwọn pẹpẹ òrìṣà yín, lórí òkè níbi tí ẹ ti ń sìn: Èmi yóò sì kó òkú yín jọ, sórí àwọn òkú òrìṣà yín. Èmi ó sì kóríra yín.

31. Èmi yóò sọ àwọn ìlú yín di ahoro, èmi yóò sì ba àwọn ilé mímọ́ yín jẹ́. Inú mi kì yóò sì dùn sí òórùn ọrẹ yín mọ́.

32. Èmi yóò pa ilẹ̀ yín run débi pé ẹnu yóò ya àwọn ọ̀ta yín tí ó bá gbé ilẹ̀ náà.

Ka pipe ipin Léfítíkù 26