Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 26:16-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Èmi yóò se àwọn nǹkan wọ̀nyí sí yín: Èmi yóò mú ìpáyà òjijì bá yín: àwọn àrùn afinisòfò, àti ibà afọ́nilójú, tí í pani díẹ̀díẹ̀. Ẹ̀yin yóò gbin èso ilẹ̀ yín lásán: nítorí pé àwọn ọ̀ta yín ni yóò jẹ gbogbo ohun tí ẹ̀yin ti gbìn.

17. Èmi yóò dojú kọ yín títí tí ẹ̀yin ó fi di ẹni ìkọlù; àwọn tí ó kóríra yín ni yóò sì ṣe àkóso lórí yín. Ìbẹ̀rù yóò mú yín débi pé ẹ̀yin yóò máa sá kákìkiri nígbà tí ẹnikẹ́ni kò lé yín.

18. “ ‘Bí ẹ̀yin kò bá wá gbọ́ tèmi lẹ́yìn gbogbo èyí: Èmi yóò fi kún ìyà yín ní ìlọ́po méje nítorí ẹ̀ṣẹ̀ yín.

19. Èmi yóò fọ́ agbára ìgbéraga yín: ojú ọ̀run yóò le koko bí irin: ilẹ̀ yóò sì le bí idẹ (òjò kò ní rọ̀: ilẹ̀ yín yóò sì le).

20. Ẹ ó máa lo agbára yín lásán torí pé ilẹ̀ yín kì yóò so èso, bẹ́ẹ̀ ni àwọn igi yín kì yóò so èso pẹ̀lú.

21. “ ‘Bí ẹ bá tẹ̀ṣíwájú láì gbọ́ tèmi, Èmi yóò tún fa ìjayà yín le ní ìgbà méje gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ yín.

Ka pipe ipin Léfítíkù 26