1. Olúwa sọ fún Mósè pé,
2. “Bá gbogbo àpéjọpọ̀ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sọ̀rọ̀, sì wí fún wọn pé: ‘Ẹ jẹ́ mímọ́ nítorí Èmi Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ mímọ́.
3. “ ‘Ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ bọ̀wọ̀ fún ìyá àti bàbá rẹ̀, kí ẹ sì ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
4. “ ‘Ẹ má ṣe yípadà tọ ère òrìsà lẹ́yìn, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọdọ̀ rọ ère òrìsà idẹ fún ara yín. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
5. “ ‘Nígbà tí ẹ̀yín bá sì rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa, kí ẹ̀yin kí ó se é ní ọ̀nà tí yóò fi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà dípò yín!
6. Ní ọjọ́ tí ẹ bá rú u náà ni ẹ gbọdọ̀ jẹ ẹ́ tàbí ní ọjọ́ kejì; èyí tí ó bá sẹ́kù di ọjọ́ kẹta ni kí ẹ fi iná sun.
7. Bí ẹ bá jẹ nínú èyí tí ó sẹ́kù di ọjọ́ kẹta, àìmọ́ ni èyí jẹ́, kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà.