Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 18:9-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin rẹ tí ó jẹ́ ọmọ ìyá rẹ lòpọ̀, yálà a bí i nílé yín tàbí lóde.

10. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin, ọmọ rẹ ọkùnrin lòpọ̀ tàbí ọmọbìnrin ọmọ rẹ obìnrin lòpọ̀ nítorí pé ìhòòhò wọn, ìhòòhò ìwọ fúnrarẹ ni.

11. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin aya bàbá rẹ lòpọ̀; èyí tí a bí fún bàbá rẹ nítorí pé arábìnrin rẹ ni

12. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin bàbá rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan bàbá rẹ ni.

13. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin mọ̀mọ́ rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan ìyá rẹ ni.

14. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù u arákùnrin bàbá rẹ: nípa sísun mọ́ aya rẹ̀ láti bá a lòpọ̀ nítorí pé ìyàwó ẹ̀gbọ́n bàbá rẹ ni.

15. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọ àna obìnrin rẹ lòpọ̀ nítorí pé aya ọmọ rẹ ni. Má ṣe bá a lòpọ̀.

Ka pipe ipin Léfítíkù 18