Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 18:1-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Olúwa sọ fún Mósè pé:

2. “Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé: ‘èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.

3. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe bí wọ́n ti ń ṣe ní Éjíbítì níbi tí ẹ ti gbé rí: bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe bí wọ́n ti ń ṣe ní ilẹ̀ Kénánì níbi tí èmi ń mú yín lọ. Ẹ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé iṣe wọn.

4. Ẹ gbọdọ̀ tẹ̀lé òfin mi kí ẹ sì kíyèsí àti pa àṣẹ mi mọ́.

5. Ẹ pa àṣẹ àti òfin mi mọ́. Ẹni tí ó bá ṣe ìgbọ́ràn sí wọn yóò máa gbé nípa wọn, Èmi ni Olúwa.

6. “ ‘Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ súnmọ́ ìbátan rẹ̀ láti bá a lòpọ̀, èmí ni Olúwa.

7. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù u bàbá rẹ nípa bíbá ìyá rẹ lòpọ̀, ìyá rẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ bá a lòpọ̀.

8. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù u bàbá rẹ nípa bíbá ìyàwó bàbá rẹ lòpọ̀: nítorí ìhòòhò bàbá rẹ ni.

9. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin rẹ tí ó jẹ́ ọmọ ìyá rẹ lòpọ̀, yálà a bí i nílé yín tàbí lóde.

10. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin, ọmọ rẹ ọkùnrin lòpọ̀ tàbí ọmọbìnrin ọmọ rẹ obìnrin lòpọ̀ nítorí pé ìhòòhò wọn, ìhòòhò ìwọ fúnrarẹ ni.

11. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin aya bàbá rẹ lòpọ̀; èyí tí a bí fún bàbá rẹ nítorí pé arábìnrin rẹ ni

12. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin bàbá rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan bàbá rẹ ni.

13. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin mọ̀mọ́ rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan ìyá rẹ ni.

14. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù u arákùnrin bàbá rẹ: nípa sísun mọ́ aya rẹ̀ láti bá a lòpọ̀ nítorí pé ìyàwó ẹ̀gbọ́n bàbá rẹ ni.

15. “ ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọ àna obìnrin rẹ lòpọ̀ nítorí pé aya ọmọ rẹ ni. Má ṣe bá a lòpọ̀.

Ka pipe ipin Léfítíkù 18