Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 14:50-56 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

50. Yóò sì pa ọ̀kan nínú àwọn ẹyẹ náà sorí omi tí ó mọ́ nínú ìkòkò amọ̀.

51. Kí ó ri igi sídà, hísópù, òdòdó àti ààyè ẹyẹ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ òkú ẹyẹ àti omi tí ó mọ́ náà kí ó fi wọ́n ilẹ náà lẹ́ẹ̀méje.

52. Yóò fi ẹ̀jẹ̀ ẹyẹ náà, omi tí ó mọ́, ààyè ẹyẹ, igi sídà, hisopu àti òdòdó sọ ilé náà di mímọ́.

53. Kí àlùfáà ju ààyè ẹyẹ náà sílẹ̀ lẹ́yìn ìlú. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún ilé náà. Ilé náà yóò sì mọ́.”

54. Àwọn wọ̀nyí ni ìlànà fún èyíkéyí àrùn àwọ̀ ara tí ó le è ràn ká (ẹ̀tẹ̀), fún làpálàpá,

55. fún ẹ̀tẹ̀ nínú aṣọ, tàbí ilé,

56. fún ìwú, fún èélá àti ibi ara dídán.

Ka pipe ipin Léfítíkù 14