Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 14:48-57 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

48. “Bí àlùfáà bá wá yẹ̀ ẹ́ wò tí àrùn náà kò gbilẹ̀ mọ́ lẹ́yìn tí a ti rẹ́ ilé náà: kí àlùfáà pe ilé náà ní mímọ́, torí pé àrùn náà ti lọ.

49. Láti sọ ilé yìí di mímọ́. Àlùfáà yóò mú ẹyẹ méjì àti igi sídà òdòdó àti hísópù.

50. Yóò sì pa ọ̀kan nínú àwọn ẹyẹ náà sorí omi tí ó mọ́ nínú ìkòkò amọ̀.

51. Kí ó ri igi sídà, hísópù, òdòdó àti ààyè ẹyẹ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ òkú ẹyẹ àti omi tí ó mọ́ náà kí ó fi wọ́n ilẹ náà lẹ́ẹ̀méje.

52. Yóò fi ẹ̀jẹ̀ ẹyẹ náà, omi tí ó mọ́, ààyè ẹyẹ, igi sídà, hisopu àti òdòdó sọ ilé náà di mímọ́.

53. Kí àlùfáà ju ààyè ẹyẹ náà sílẹ̀ lẹ́yìn ìlú. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún ilé náà. Ilé náà yóò sì mọ́.”

54. Àwọn wọ̀nyí ni ìlànà fún èyíkéyí àrùn àwọ̀ ara tí ó le è ràn ká (ẹ̀tẹ̀), fún làpálàpá,

55. fún ẹ̀tẹ̀ nínú aṣọ, tàbí ilé,

56. fún ìwú, fún èélá àti ibi ara dídán.

57. Láti mú kí a mọ̀ bóyá nǹkan mọ́ tàbí kò mọ́.Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún àrùn àwọ̀ ara tí ó ń ràn ká àti ẹ̀tẹ̀.

Ka pipe ipin Léfítíkù 14