Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 9:9-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Wọ́n sì dáhùn pé: “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Éjíbítì,

10. àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Ámórì méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jọ́dánì, sí Síhónì ọba Héṣíbónì, àti Ógù ọba Básánì, tí wọ́n jọba ní Áṣítarótù.

11. Àwọn àgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.” ’

12. Gbígbóná ní a mú oúnjẹ ní ojí nílé ní oji tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsinyí.

13. Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Asọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jínjìn.”

14. Àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.

15. Nígbà náà ni Jósúà ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.

16. Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gíbíónì, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.

17. Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹ́ta: Gíbíónì, Kéfírà, Béérótù àti Kiriati-jéárímù.

18. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbààgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì.Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbààgbà náà,

19. ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsinyí.

Ka pipe ipin Jóṣúà 9