Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 9:6-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Wọ́n sì tọ Jóṣúà lọ ní ibùdó ní Gílígálì, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”

7. Àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì sọ fún àwọn ará Hífì pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè se àdéhùn pẹ̀lú yín?”

8. “Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Jóṣúà.Ṣùgbọ́n Jóṣúà béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yín ti wá?”

9. Wọ́n sì dáhùn pé: “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Éjíbítì,

10. àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Ámórì méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jọ́dánì, sí Síhónì ọba Héṣíbónì, àti Ógù ọba Básánì, tí wọ́n jọba ní Áṣítarótù.

11. Àwọn àgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.” ’

12. Gbígbóná ní a mú oúnjẹ ní ojí nílé ní oji tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsinyí.

13. Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Asọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jínjìn.”

Ka pipe ipin Jóṣúà 9