Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 4:19-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Ní ọjọ́ kẹwàá (10) osù kìn-ní-ní (1) àwọn ènìyàn náà lọ láti Jọ́dánì, wọ́n sì dúró ní Gílígálì ní ìlà-oòrùn Jẹ́ríkò.

20. Jóṣúà sì to àwọn òkúta méjìlá (12) tí wọ́n mú jáde ní Jọ́dánì jọ ní Gílígálì.

21. Ó sì sọ fún àwọn ará Ísírẹ́lì, “Ní ọjọ́ iwájú nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè ní ọwọ́ baba wọn pé, ‘Kí ni òkúta wọ̀nyí yìí dúró fún?’

22. Nígbà náà ni ẹ ó jẹ́ kí àwọn ọmọ yín mọ̀ pé, ‘Ísírẹ́lì rékọjá odò Jọ́dánì ní orí ilẹ̀ gbígbẹ.’

23. Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín mú Jọ́dánì gbẹ ní iwájú u yín títí ẹ̀yin fi kọjá. Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí Jọ́dánì gẹ́gẹ́ bí ó ti se sí Òkun Pupa, nígbà tí ó mú un gbẹ ní iwájú wa títí àwa fi kọjá.

24. Ó ṣe èyí kí gbogbo ayé lè mọ̀ pé ọwọ́ Olúwa ní agbára, àti kí ẹ̀yin kí ó lè máa bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín ní ìgbà gbogbo.”

Ka pipe ipin Jóṣúà 4