Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 4:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọjá nínú odò Jọ́dánì tan, Olúwa ṣọ fún Jóṣúà pé,

2. “Yan ọkùnrin méjìlá (12) nínú àwọn ènìyàn, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,

3. kí o sì pàṣẹ fún wọn pé Ẹ gbé òkúta méjìlá (12) láti àárin odò Jọ́dánì ní ibi tí àwọn àlùfáà dúró sí, kí ẹ sì rù wọn kọjá, kí ẹ sì gbé wọn sí ibi tí ẹ̀yin yóò sùn ní alẹ́ yìí.”

4. Bẹ́ẹ̀ ni Jóṣúà pe àwọn ọkùnrin méjìlá (12) tí ó ti yàn nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kàn,

5. ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kọjá lọ ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín sí àárin odò Jọ́dánì. Kí olúkúlùkù yín gbé òkúta kọ̀ọ̀kan lé èjìká a rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Ísírẹ́lì,

6. kí ó sì jẹ́ àmì láàrin yín. Ní ọjọ́ iwájú, nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ ọ yín pé, ‘Kí ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’

7. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò dá wọn lóhùn pé, nítorí a gé omi odò Jọ́dánì kúrò ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí a rékọjá a Jọ́dánì, a gé omi Jọ́dáni kúrò. Àwọn òkúta wọ̀nyí yóò sì jẹ́ ìrántí fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì láéláé.”

Ka pipe ipin Jóṣúà 4