Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 21:26-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kóhátì.

27. Àwọn ọmọ Gáṣóní idile àwọn ọmọ Lefi ní wọ́n fún lára:“ìdajì ẹ̀yà Mánásè,Gólánì ní Básánì (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be Ésítarà pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ méjì;

28. Láti ara ẹ̀yà Ísákárì ni wọ́n ti fún wọn ní,Kísíónì Dábérátì,

29. Járímútì àti Ẹni Gánímù, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ mẹ́rin.

30. Láti ara ẹ̀yà Ásíérì ni wọ́n ti fún wọn níMísálì, àti Ábídónì,

31. Hélíkátì àti Réhóbì, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ mẹ́rin;

32. Láti ara ẹ̀yà Náfítanì ni a ti fún wọn níKedeṣì ní Gálílì (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Hámótì Dórì àti Kárítanì, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́ta.”

33. Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gáṣónì jẹ́ mẹ́talá, pẹ̀lú ilẹ́ pápá oko wọn.

34. Láti ara ẹ̀yà Sébúlónì ni a ti fún ìdílé Mérárì (tí í ṣe ìyókù ọmọ Léfì) ní:“Jókíníámù, Kárítà,

Ka pipe ipin Jóṣúà 21