Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 21:15-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Hólónì àti Débírì,

16. Háínì, Jútà àti Bẹti-Sẹ́mẹ́sì, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn. Ìlú mẹ́sàn án láti ara ẹ̀yà méjì wọ̀nyí.

17. Láti ara ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì ni wọ́n ti fún wọn ní Gíbíónì, Gẹ́bà,

18. Ánatótì àti Álímónì, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.”

19. Gbogbo ìlú àwọn àlùfáà, ìran Árónì, jẹ́ mẹ́talá, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá wọn.

20. Ìyòókù ìdílé Kóhátì tí ó jẹ́ ọmọ Léfì ní a pín ìlú fún láti ara ẹ̀yà Éfúráímù.

21. “Ní ilẹ̀ òkè Éfúráímù wọ́n fún wọn ní Ṣẹ́kẹ́mù (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn) ati Gésérì,

22. Kíbásáímù àti Bẹti-Hórónì, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.

23. Láti ara ẹ̀yà Dánì ní wọ́n ti fún wọn ní Élítékè Gíbátónì,

24. Áíjálónìd àti Gati-Rímónì, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ mẹ́rin.

25. Láti ara ìdajì ẹ̀yà Mánásè ní wọ́n ti fún wọn ní Tánákì àti Gati-Rímónì pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú méjì.”

26. Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kóhátì.

27. Àwọn ọmọ Gáṣóní idile àwọn ọmọ Lefi ní wọ́n fún lára:“ìdajì ẹ̀yà Mánásè,Gólánì ní Básánì (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be Ésítarà pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ méjì;

28. Láti ara ẹ̀yà Ísákárì ni wọ́n ti fún wọn ní,Kísíónì Dábérátì,

Ka pipe ipin Jóṣúà 21