Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 2:14-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. “Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”

15. Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.

16. Ó sì ti ṣọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má baà rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”

17. Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa baà lè mọ́ kúró nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.

18. Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò ṣo okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.

19. Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú ù rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní órí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.

Ka pipe ipin Jóṣúà 2