Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 11:3-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. sí àwọn ará Kénánì ní ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn; sí àwọn Ámórì, Hítì, Pérísì àti Jébúsì ní orí òkè; àti sí àwọn Hífì ní ìsàlẹ̀ Hámónì ní agbégbé Mísípà.

4. Wọ́n sì jáde pẹ̀lú gbogbo ogun wọn àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹsin àti kẹ̀kẹ́ ogun ńlá, wọ́n sì pọ̀, gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun

5. Gbogbo àwọn ọba yìí pa ọmọ ogun wọn pọ̀, wọ́n sì pa ibùdó sí ibi omi Mérómù láti bá Ísírẹ́lì jà.

6. Olúwa sì sọ fún Jóṣúà pé, “Má ṣe bẹ̀rù wọn nítorí ní àkókò yìí ní ọ̀la, gbogbo wọn ni èmi yóò fi lé Ísírẹ́lì lọ́wọ́ ní pípa. Ìwọ yóò já iṣan ẹ̀yìn ẹṣin wọn, ìwọ yóò sì sun kẹ̀kẹ́ ogun wọn.”

7. Bẹ́ẹ̀ ni Jóṣúà àti gbogbo àwọn ọmọ ogun rẹ̀ yọ sí wọn ní òjijì ní ibi omi Meromù, wọ́n sì kọlù wọ́n,

Ka pipe ipin Jóṣúà 11