1. Nígbà tí Jábínì ọba Hásórù gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó ránṣẹ́ sí Jóbábù ọba Madónì, sí ọba Ṣímírónì àti Ákíṣáfù,
2. àti sí àwọn ọba ìhà àríwá tí wọ́n wà ní orí òkè ní aginjù, gúsù ti Kínérótù, ní ẹsẹ̀ òkè ìwọ̀-oòrùn àti ní Nafotu Dórì ní ìwọ̀-oòrùn;
3. sí àwọn ará Kénánì ní ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn; sí àwọn Ámórì, Hítì, Pérísì àti Jébúsì ní orí òkè; àti sí àwọn Hífì ní ìsàlẹ̀ Hámónì ní agbégbé Mísípà.