1. Lẹ́yìn ikú u Móṣè ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Jóṣúà ọmọ Núnì, olùrànlọ́wọ́ ọ Móṣè:
2. “Mósè ìránṣẹ́ ẹ̀ mi ti kú. Nísinsìn yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí; ẹ múra láti kọjá odò Jọ́dánì lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Ísírẹ́lì.
3. Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹṣẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Móṣè.