Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 9:8-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Òun nìkanṣoṣo ni ó na ojú ọ̀run lọ,ti ó sì ń rìn lórí ìgbì òkun.

9. Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Béárì, Óríónìàti Píléíádè àti yàrá púpọ̀ ti gúsù.

10. Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwàrí lọ,àní ohun ìyanu láìní iye.

11. Kíyèsí i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi,èmi kò sì rí i, ó sì kọjá síwáju,bẹ́ẹ̀ ni èmi kò rí ojú rẹ̀.

12. Kiyèsí i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà?Ta ni yóò bi í pé kí ni ìwọ ń ṣe nì?

13. Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn,àwọn oní rànlọ́wọ́ ti Ráhábù a sì tẹriba lábẹ́ rẹ̀.

14. “Kí ní ṣe tí èmi ò fi dá a lóhùn?Tí èmi kò fi máa fi ọ̀rọ̀ àwàwí mi ṣe àwsíyé fún-un?

15. Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi,èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn,ṣùgbọ́n èmi ó gbàdúrà fún àánú.

Ka pipe ipin Jóòbù 9