Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 9:6-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀,ọwọ̀n rẹ̀ sì mì tìtì

7. Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è rànkí ó sì dí ìmọ́lẹ̀ ìràwọ̀ mọ́.

8. Òun nìkanṣoṣo ni ó na ojú ọ̀run lọ,ti ó sì ń rìn lórí ìgbì òkun.

9. Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Béárì, Óríónìàti Píléíádè àti yàrá púpọ̀ ti gúsù.

10. Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwàrí lọ,àní ohun ìyanu láìní iye.

11. Kíyèsí i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi,èmi kò sì rí i, ó sì kọjá síwáju,bẹ́ẹ̀ ni èmi kò rí ojú rẹ̀.

12. Kiyèsí i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà?Ta ni yóò bi í pé kí ni ìwọ ń ṣe nì?

13. Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn,àwọn oní rànlọ́wọ́ ti Ráhábù a sì tẹriba lábẹ́ rẹ̀.

14. “Kí ní ṣe tí èmi ò fi dá a lóhùn?Tí èmi kò fi máa fi ọ̀rọ̀ àwàwí mi ṣe àwsíyé fún-un?

15. Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi,èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn,ṣùgbọ́n èmi ó gbàdúrà fún àánú.

16. Bí èmi bá sì ké pè é, tí Òun sì dá mi lóhùn,èmi kì yóò sì gbàgbọ́ pé, Òun ti fetí sí ohùn mi.

Ka pipe ipin Jóòbù 9