Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 9:28-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Ẹ̀rù ìbànújẹ́ mi gbogbo bà mí,èmi mọ̀ pé ìwọ kì yóò mú mi bí aláìṣẹ̀.

29. Bí ó bá ṣe pé ènìyàn búburú ni èmi,ǹjẹ́ kí ni èmi ń ṣe làálàá lásán sí?

30. Bí mo tilẹ̀ fi ọṣẹ ojú dídì wẹ ara mi,tí mo fi omi àrò wẹ ọwọ́ mi mọ́,

31. ṣíbẹ̀ ìwọ ó gbé mi wọ inú ihòọ̀gọ̀dọ̀ aṣọ ara mi yóò sọ mi di ìríra.

32. “Nítorí Òun kì í ṣe ènìyàn bí èmi,tí èmi ó fi dá a lóhùn tí àwa o fi pàdé ní ìdájọ́.

33. Bẹ́ẹ̀ ni kò sí alátúnṣe kan ní agbede-méjì watí ìbá fi ọwọ́ rẹ̀ lé àwa méjèèjì lára.

34. Kí ẹnìkan ṣá à mú ọ̀pá Ọlọ́run kúrò lára mi,kí ìbẹ̀rù rẹ̀ kí ó má sì se dáyà fò mí

35. Nígbà náà ni èmi ìbá sọ̀rọ̀, èmi kì bá sì bẹ̀rù rẹ̀;ṣùgbọ́n bí ó tí dáré-ti mi, kò ri bẹ́ẹ̀ fún mi.

Ka pipe ipin Jóòbù 9