Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 9:1-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Jóòbù sì dáhùn ó sì wí pé:

2. “Èmi mọ̀ pe bẹ́ẹ̀ ni ní òtítọ́!Báwo ní ènìyàn yóò ha ti ṣe jẹ́ aláre níwájú Ọlọ́run?

3. Bí ó bá ṣe pé yóò bá jà,òun kì yóò lè dálóhùn kan nínú ẹgbẹ̀rùn-ún ọ̀rọ̀.

4. Ọlọ́gbọ́n nínú àwọn alágbára ní ipa ní Òún;ta ni ó ṣe agídí sí i tí ó sì gbé fún rí?

5. Ẹni tí ó sí òkè nídìí tí wọn kò sì mọ́:tí ó taari wọn ṣubú ní ìbínú rẹ̀

6. Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀,ọwọ̀n rẹ̀ sì mì tìtì

7. Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è rànkí ó sì dí ìmọ́lẹ̀ ìràwọ̀ mọ́.

8. Òun nìkanṣoṣo ni ó na ojú ọ̀run lọ,ti ó sì ń rìn lórí ìgbì òkun.

9. Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Béárì, Óríónìàti Píléíádè àti yàrá púpọ̀ ti gúsù.

10. Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwàrí lọ,àní ohun ìyanu láìní iye.

11. Kíyèsí i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi,èmi kò sì rí i, ó sì kọjá síwáju,bẹ́ẹ̀ ni èmi kò rí ojú rẹ̀.

12. Kiyèsí i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà?Ta ni yóò bi í pé kí ni ìwọ ń ṣe nì?

Ka pipe ipin Jóòbù 9