Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 8:3-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí,tàbí Olódùmárè a máa fi òtítọ́ sẹ̀ bí?

4. Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ sẹ̀ sí i,ó sì gbá wọn kúrò nítorí àṣẹ wọn.

5. Bí ìwọ bá sì képe Ọlọ́run ní ìgbà àkókò,tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmáarè.

6. Ìwọ ìbá mọ́, kí ó sì dúró sinṣsin:ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsìn yìí òun yóò tají fún ọ,òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.

7. Ìpilẹsẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í,bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yin rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.

8. “Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, bèèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nìkí o sì kíyèsí ìwádìí àwọn baba wọn.

9. Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan,nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.

10. Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ?Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?

11. Koríko odò ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀tàbí èèsú ha lè dàgbà láìlómi?

12. Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò kee lulẹ̀,ó rọ dànù, ewéko mìíràn gbogbo hù dípò rẹ̀

Ka pipe ipin Jóòbù 8