Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 8:11-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Koríko odò ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀tàbí èèsú ha lè dàgbà láìlómi?

12. Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò kee lulẹ̀,ó rọ dànù, ewéko mìíràn gbogbo hù dípò rẹ̀

13. Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run,àbá àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.

14. Àbá ẹni tí a ó ké kúrò,àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dà bí ilé aláǹtakùn.

15. Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró,yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́

16. Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú òòrùn,ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.

17. Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká,ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.

18. Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀,nígbà náà ni ipò náà sẹ́ ẹ pé, ‘Èmi kò ri ọ rí!’

19. Kíyèsí i, ayé rẹ̀ gbẹ dànùàti lati inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmìíràn yóò hù jáde wá.

Ka pipe ipin Jóòbù 8