Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 6:4-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Nítorí pé ọfà Olódùmárè wọ̀ mi nínú,oró èyí tí ọkàn mi mú;ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.

5. Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́ á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko,tàbí ọ̀dá-màlúù a máa dún sórí ìjẹ rẹ̀?

6. A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀,tàbi adùn ha wà nínú fúnfún eyin?

7. Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò,òun ni ó dàbí oúnjẹ mi tí kò ní adùn.

8. “Áà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà;àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi.

9. Àní Ọlọ́rin ìbá jẹ́ pa mí run,tí òun ì bá jẹ́ siwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò.

10. Nígbà náà ní èmi ì bá ní ìtùnú síbẹ̀,àní èmi ì bá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí:nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí.

11. “Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí?Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù?

12. Agbára mi iṣe agbára òkúta bí,tàbí ẹran ara iṣe idẹ?

13. Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi:ọgbọ́n ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?

14. “Ẹni tí àyà rẹ̀ yọ́ dànù, ta ni a bá máa ṣàánú fún láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ wá,kí ó má ba à kọ ìbẹ̀rù Olódumáarè sílẹ̀?

15. Àwọn ará mi ṣọ̀tẹ̀ bí odò sólobí ìṣàn gúru omi odò sólo, wọ́n ṣàn kọjá lọ.

16. Tí ó dúdú nítorí omi dídì,àti níbi tí odò dídì gbé lùmọ̀ sí.

17. Nígbà kúgbà tí wọ́n bá gbóná wọn a sì yọ́ ṣànlọ,nígbà tí òòrùn bá mú, wọn a sì gbẹ kúrò ni ipò wọn.

18. Ìyà ọ̀nà wọn a sì yípadà sí apá kan,wọ́n gòkè sí ibi asán, wọ́n sì run.

19. Ẹgbẹ́ ogun Témà ń wòyeàwọn ọwọ́ àrò Sébà ń dúró dè wọ́n.

Ka pipe ipin Jóòbù 6