Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 6:2-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. “Áà! à bá lè wọ̀n ìbìnújẹ́ mi nínú òṣùwọ̀n,kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òṣùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀!

3. Ǹjẹ́ nísinsìn yìí, ìbá wúwo jú iyánrìn òkun lọ:nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé

4. Nítorí pé ọfà Olódùmárè wọ̀ mi nínú,oró èyí tí ọkàn mi mú;ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.

5. Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́ á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko,tàbí ọ̀dá-màlúù a máa dún sórí ìjẹ rẹ̀?

6. A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀,tàbi adùn ha wà nínú fúnfún eyin?

7. Ohun ti ọ̀kan mi kọ̀ láti tọ́wò,òun ni ó dàbí oúnjẹ mi tí kò ní adùn.

8. “Áà! èmi ìbá lè rí ìbéèrè mi gbà;àti pé, kí Ọlọ́run lè fi ohun tí èmi ṣàfẹ́rí fún mi.

9. Àní Ọlọ́rin ìbá jẹ́ pa mí run,tí òun ì bá jẹ́ siwọ́ rẹ̀ kì ó sì ké mi kúrò.

10. Nígbà náà ní èmi ì bá ní ìtùnú síbẹ̀,àní èmi ì bá mú ọkàn mi le nínú ìbànújẹ́ mi ti kò dá ni sí:nítorí èmi kò fi ọ̀rọ̀ ẹni mímọ́ ni sin rí.

11. “Kí ní agbára mi tí èmi ó fi retí?Kí sì ní òpin mi tí èmi ó fi ní sùúrù?

12. Agbára mi iṣe agbára òkúta bí,tàbí ẹran ara iṣe idẹ?

13. Ìrànlọ́wọ́ mi kò ha wà nínú mi:ọgbọ́n ha ti sálọ kúrò lọ́dọ̀ mi bí?

Ka pipe ipin Jóòbù 6