Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 6:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Jóòbù sì dáhùn ó si wí pé:

2. “Áà! à bá lè wọ̀n ìbìnújẹ́ mi nínú òṣùwọ̀n,kí a sì le gbé ọ̀fọ̀ mi lé orí òṣùwọ̀n ṣọ̀kan pọ̀!

3. Ǹjẹ́ nísinsìn yìí, ìbá wúwo jú iyánrìn òkun lọ:nítorí náà ni ọ̀rọ̀ mi ṣe ń tàsé

4. Nítorí pé ọfà Olódùmárè wọ̀ mi nínú,oró èyí tí ọkàn mi mú;ìpayà-ẹ̀rù Ọlọ́run dúró tì mí.

5. Ǹjẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́ á máa dún nígbà tí ó bá ní koríko,tàbí ọ̀dá-màlúù a máa dún sórí ìjẹ rẹ̀?

6. A ha lè jẹ ohun tí kò ní adùn ní àìní iyọ̀,tàbi adùn ha wà nínú fúnfún eyin?

Ka pipe ipin Jóòbù 6