Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 5:16-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún talákààìsòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.

17. “Kíyèsíi, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí,nítorí náà, má ṣe gan ìbàwí Olódùmarè.

18. Nítorí pé òun a mú ni lára kan,a sì di ìdì ìtura, ó ṣá lọ́gbẹ́, ọwọ́ rẹ̀ á sì mú jìnnà.

19. Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà,àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ

20. Nínu ìyànu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikúàti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.

21. A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́nbẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.

22. Ìrin ìparun àti ti ìyàn ni ìwọ yóò rìnbẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.

23. Nitorí pé ìwọ ó bá òkúta ìgbẹ́ múlẹ̀,àwọn ẹranko ìgbẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.

24. Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wàìwọ yóò sì máa ṣe ìbẹ̀wò ibùjókòó rẹ, ìwọ kì yóò sìnà.

25. Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú ọmọ rẹ ó sì pọ̀àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ yóò rí bí koríko ìgbẹ́.

Ka pipe ipin Jóòbù 5