Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 5:10-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayétí ó sì ń rán omi sí ilẹ̀ẹ́lẹ̀.

11. Láti gbé àwọn orilẹ̀ èdè lékèkí á lè gbé àwọn ẹni ìbànújẹ́ ga sí ibi aláìléwu.

12. Ó yí ìmọ̀ àwọn alárèékérekè po,bẹ́ẹ̀ ní ọwọ́ wọn kò lè mú ìdàwọ́lé wọn sẹ.

13. Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú arékerekè ara wọn,àti ìmọ̀ àwọn òǹrorò ní ó tari ṣubú ní ògèdèǹgbé.

14. Wọ́n sáre wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sánwọ́n sì fọwọ́ tálẹ̀ ní ọ̀sán gangan bí ẹni pé ní òru.

15. Ṣùgbọ́n ó gba talákà là ní ọwọ́ idà,lọ́wọ́ ẹnu wọn àti lọ́wọ́ àwọn alágbára.

16. Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún talákààìsòótọ́ sì pa ẹnu rẹ̀ mọ́.

17. “Kíyèsíi, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí,nítorí náà, má ṣe gan ìbàwí Olódùmarè.

18. Nítorí pé òun a mú ni lára kan,a sì di ìdì ìtura, ó ṣá lọ́gbẹ́, ọwọ́ rẹ̀ á sì mú jìnnà.

19. Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà,àní nínú méje, ibi kan kì yóò bá ọ

20. Nínu ìyànu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikúàti nínú ogun, yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ idà.

21. A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́nbẹ́ẹ̀ ní ìwọ kì yóò bẹ̀rù ìparun tí ó bá dé.

22. Ìrin ìparun àti ti ìyàn ni ìwọ yóò rìnbẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò bẹ̀rù ẹranko ilẹ̀ ayé.

23. Nitorí pé ìwọ ó bá òkúta ìgbẹ́ múlẹ̀,àwọn ẹranko ìgbẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní àlàáfíà.

Ka pipe ipin Jóòbù 5