Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 42:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ígbà náà ní Jóòbù dá Olúwa lóhùn, ó sì wí pé:

2. “Èmi mọ̀ pé, ìwọ lè e ṣe ohungbogbo, àti pé, kò si ìro inú tí a lè fa sẹ́yìn kurò lọ́dọ̀ rẹ.

3. Ìwọ béèrè, ta ni ẹni tí ń fi ìgbìmọ̀ pamọ́ làíní ìmọ̀?Nítorí náà ní èmi ṣe ń sọ èyití èmi kò mọ̀, ohun tí ó ṣe ìyànu jọjọ níwájú mi, ti èmi kò mòye.

4. “Ìwọ wí pé, ‘gbọ́ tèmi báyìí,èmi ó sì sọ; èmi óbèèrè lọ́wọ́ rẹ, ìwọ yóò sì dá mi lóhùn.’

5. Etí mi sì ti gbọ́ nípa rẹ, ṣùgbọ́nnísinsìnyí ojú mi ti rí ọ.

6. Ǹjẹ́ nítorí náà èmi kórìíra ara mi,mo sì ronúpìwàdà nínú ekuru àti eérú.”

7. Bẹ́ẹ̀ ó sì rí, lẹ́yìn ìgbàtí Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Jóòbù, Olúwa sì wí fún Élífásì, ara Témà pé, mo bínú sí ọ, àti sí àwọn ọrẹ́ rẹ méjèèjì, nítorí pé ẹ̀yin kò sọ̀rọ̀, níti èmi, ohun tí ó tọ́, bí Jóòbù ìránṣẹ́ mi ti sọ.

8. Nítorí náà, ẹ mú akọ ẹgbọ̀rọ̀ màlúù méje, àti àgbò méje, kí ẹ sì tọ̀ Jóòbù ìránṣẹ́ mi lọ, kí ẹ sì fi rú ẹbọ sísun fún ara yín; Jóòbù ìránṣẹ́ mi yóò sì gbàdúrà fún yin; nítorí pé àdúrà rẹ̀ ní èmi yóò gbà; kí èmi kí ó má ba ṣe si yín bí ìsìnà yín, níti pé ẹ̀yin kò sọ̀rọ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi bi Jóòbù ìránṣẹ́ mi ti ṣe.

Ka pipe ipin Jóòbù 42