Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 41:7-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ìwọ ha lè fi ọ̀kọ̀-irin awọ rẹ̀,tàbí orí rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ipẹja.

8. Fi ọwọ́ rẹ lée lára, ìwọ ó rántí ìjànáà, ìwọ kì yóò sì ṣe bẹ̀ẹ́ mọ́.

9. Kiyèsí àbá nípaṣẹ̀ rẹ ní asán; níkìkì ìrí rẹ̀ ara kì yóò ha rọ̀ ọ́ wẹ̀sì?

10. Kò sí ẹni aláyà lílé tí ó lè rusókè; Ǹjẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú mi.

11. Ta ni ó ṣáájú ṣe fún mi, tí èmi ìbáfi san-án fún un? Ohunkóhun ti ń bẹ lábẹ́ ọ̀run gbogbo, tèmi ni.

12. “Èmi kì yóò fi ẹ̀yà ara rẹ, tàbi ipárẹ, tàbí ìhámọ́ra rẹ tí ó ní ẹwà pamọ́.

13. Ta ni yóò lè rídìí aṣọ àpáta rẹ?Tàbí ta ni ó lè súnmọ́ ọ̀nà méjì ẹ̀yìn rẹ.?

14. Ta ni ó lè sí ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ?Àyíká ẹ̀yin rẹ ni ìbẹ̀rù ńlá.

15. Ipẹ́ lílé ní ìgbéraga rẹ̀; ó pàdépọ̀ tímọ́tímọ́ bí àmì èdìdì.

16. Èkíní fi ara mọ́ èkejì tóbẹ́ẹ̀ tí afẹ́fẹ́kò lè wọ àárin wọn.

17. Èkíní fi ara mọ́ èkejì rẹ̀; wọ́n lẹ̀wọ́n pọ̀ tí a kò lè mọ̀ wọ́n.

18. Nípa sísin rẹ̀ ìmọ́lẹ̀ mọ́, ojú rẹ̀ asì dàbí ìpénpéjú òwúrọ̀.

19. Láti ẹnu rẹ ni ọ̀wọ́ iná ti jádewá, ìpẹ́pẹ́ iná a sì ta jáde.

Ka pipe ipin Jóòbù 41