7. Ìwọ ha lè fi ọ̀kọ̀-irin awọ rẹ̀,tàbí orí rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ipẹja.
8. Fi ọwọ́ rẹ lée lára, ìwọ ó rántí ìjànáà, ìwọ kì yóò sì ṣe bẹ̀ẹ́ mọ́.
9. Kiyèsí àbá nípaṣẹ̀ rẹ ní asán; níkìkì ìrí rẹ̀ ara kì yóò ha rọ̀ ọ́ wẹ̀sì?
10. Kò sí ẹni aláyà lílé tí ó lè rusókè; Ǹjẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú mi.
11. Ta ni ó ṣáájú ṣe fún mi, tí èmi ìbáfi san-án fún un? Ohunkóhun ti ń bẹ lábẹ́ ọ̀run gbogbo, tèmi ni.
12. “Èmi kì yóò fi ẹ̀yà ara rẹ, tàbi ipárẹ, tàbí ìhámọ́ra rẹ tí ó ní ẹwà pamọ́.
13. Ta ni yóò lè rídìí aṣọ àpáta rẹ?Tàbí ta ni ó lè súnmọ́ ọ̀nà méjì ẹ̀yìn rẹ.?
14. Ta ni ó lè sí ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ?Àyíká ẹ̀yin rẹ ni ìbẹ̀rù ńlá.
15. Ipẹ́ lílé ní ìgbéraga rẹ̀; ó pàdépọ̀ tímọ́tímọ́ bí àmì èdìdì.
16. Èkíní fi ara mọ́ èkejì tóbẹ́ẹ̀ tí afẹ́fẹ́kò lè wọ àárin wọn.
17. Èkíní fi ara mọ́ èkejì rẹ̀; wọ́n lẹ̀wọ́n pọ̀ tí a kò lè mọ̀ wọ́n.
18. Nípa sísin rẹ̀ ìmọ́lẹ̀ mọ́, ojú rẹ̀ asì dàbí ìpénpéjú òwúrọ̀.