Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 41:18-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Nípa sísin rẹ̀ ìmọ́lẹ̀ mọ́, ojú rẹ̀ asì dàbí ìpénpéjú òwúrọ̀.

19. Láti ẹnu rẹ ni ọ̀wọ́ iná ti jádewá, ìpẹ́pẹ́ iná a sì ta jáde.

20. Láti imu rẹ ni èéfín ti jáde wá,bí ẹni pé láti inú ìkòkò tí a fẹ́ iná ìféfé lábẹ́ rẹ̀.

21. Èémi rẹ̀ tinábọ ẹ̀yin, ọ̀wọ́ iná sìti ẹnu rẹ̀ jáde.

22. Ní ọrún rẹ̀ ní agbára kù sí, àtiìbànújẹ́ àyà sì padà di ayọ̀ níwájú rẹ̀.

23. Jabajaba ẹran rẹ̀ dìjọ pọ̀, wọ́nmúra gírí fún ara wọn, a kò lè sí wọn nípò.

24. Àyà rẹ̀ dúró gbagigbagi bí òkúta,àní ó le bi ìyá ọlọ.

25. Nígbà tí ó bá gbé ara rẹ̀ sókè,àwọn alágbára bẹ̀rù; nítoríìbẹ̀rù ńlá, wọ́n dààmú.

26. Ọ̀kọ̀ tàbí idà, tàbi ọfà, ẹni tí ó sáa kò lè rán an.

27. Ó ká ìrin sí bi koríko gbígbẹ àtiidẹ si bi igi híhù.

28. Ọfà kò lè mú un sá; òkútakànnakánná lọ́dọ̀ rẹ̀ dàbí àkékù koríko.

29. Ó ka ẹṣin sí bí àkékù idi koríko;ó rẹ́rin-ín sí mímì ọ̀kọ̀.

30. Òkúta mímú ń bẹ nísàlẹ̀ abẹ́ rẹ̀, ósì tẹ́ ohun mímú ṣónṣó sórí ẹrẹ̀.

31. Ó mú ibú omi hó bí ìkòkò; ó sọ̀agbami òkun dàbí kólòbó ìkunra.

32. Ó mú ipa ọ̀nà tan lẹ́yìn rẹ̀; ènìyàna máa ka ibú sí ewú arúgbó.

33. Lórí ilẹ̀ ayé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀,tí a dá láìní ìbẹ̀rù.

34. Ó bojú wo ohun gíga gbogbo, ósì nìkan já sí ọba lórí gbogboàwọn ọmọ ìgbéraga.”

Ka pipe ipin Jóòbù 41