Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 41:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Ǹjẹ́ ìwọ lè ífi ìwọ fa Lefíátanì,ọ̀nì ńlá jáde? Tàbí ìwọ lè fi okùn so ahọ́n rẹ̀ mọ́lẹ̀?

2. Ìwọ lè fi okùn bọ̀ ọ́ ní ímú,tàbí fi ìwọ̀ gun ní ẹ̀rẹ̀kẹ́?

3. Òun ha jẹ́ bẹ ẹ̀bẹ̀ fún àánú lọ́dọ̀rẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ bí òun ha bá ọ sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́?

4. Òun ha bá ọ dá májẹ̀mú bí? Ìwọ óha máa mú ṣe ẹrú láéláé bí?

5. Ìwọ hà lè ba saré bí ẹni pé ẹyẹ ni,tàbí ìwọ ó dè é fún àwọn ọmọbìnrin ìránṣẹ́ rẹ̀?

6. Ẹgbẹ́ àwọn apẹja yóò ha máa tà ábí? Wọn ó ha pín láàrin àwọn oníṣòwò?

7. Ìwọ ha lè fi ọ̀kọ̀-irin awọ rẹ̀,tàbí orí rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ipẹja.

Ka pipe ipin Jóòbù 41