Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 40:8-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. “Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán?Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo

9. Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lèfi ohùn sán àrá bí òun?

10. Fi ọlá ńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ararẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bi ara ní aṣọ.

11. Mú ìrúnu ìbínú rẹ jáde; kíyèsígbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀

12. Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyànkí o sì rẹ ẹ sílẹ̀, kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.

13. Sin gbogbo wọn pa pọ̀ nínúerùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú

14. Nígbà náà ní èmi ó yàn ọ́ pé,ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.

15. “Ǹjẹ́ nísinsìnyí kíyèsí Béhámótì tímo dá pẹ̀lú rẹ: òun ha máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.

16. Wò o nísinsìnyí, agbára rẹ wà níẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.

17. Òun a máa jù ìru rẹ̀ bí i igikédarì; Isan itan rẹ̀ dijọ pọ̀.

18. Egungun rẹ̀ ní ògùsọ̀ idẹ;Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.

19. Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́Ọlọ́run; ṣíbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.

20. Nítòótọ́ òkè ńláńlá ní imu ohunjíjẹ fún un wá, níbi tí gbogboẹranko ìgbẹ́ máa siré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀

21. Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótósì,lábẹ́ èèsún àti ẹrẹ̀.

22. Igi lótósì síji wọn bò o;igi àrọ̀rọ̀ odò yí i kákiri.

23. Kíyèsí i, odò ńlá sàn jọjọ,òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí óbá ṣe pé odò Jọ́rdánì ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.

24. Ẹnìkan ha lè ímú u ní ojú rẹ̀, tàbía máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?

Ka pipe ipin Jóòbù 40