14. Nígbà náà ní èmi ó yàn ọ́ pé,ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
15. “Ǹjẹ́ nísinsìnyí kíyèsí Béhámótì tímo dá pẹ̀lú rẹ: òun ha máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
16. Wò o nísinsìnyí, agbára rẹ wà níẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
17. Òun a máa jù ìru rẹ̀ bí i igikédarì; Isan itan rẹ̀ dijọ pọ̀.
18. Egungun rẹ̀ ní ògùsọ̀ idẹ;Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
19. Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́Ọlọ́run; ṣíbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20. Nítòótọ́ òkè ńláńlá ní imu ohunjíjẹ fún un wá, níbi tí gbogboẹranko ìgbẹ́ máa siré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀
21. Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótósì,lábẹ́ èèsún àti ẹrẹ̀.
22. Igi lótósì síji wọn bò o;igi àrọ̀rọ̀ odò yí i kákiri.