Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 37:1-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Ayà sì fò mi si èyí pẹ̀lú, ósì kúro ní ìpò rẹ̀.

2. Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀, kí ẹ sì gbọ́ ìróohùn rẹ̀, àti èyí tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde wá.

3. Ó ṣe ìlànà rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ọ̀run gbogbo,Mọ̀nàmọ́ná rẹ̀ ni ó sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́ dé òpin ilẹ̀ ayé.

4. Lẹ́yìn mọ̀nàmọ́ná Òun kan fọ̀ramúramù; ó sì fi ohùn ọláńlárẹ̀ sán àrá; òhun kì yóò sì dáàrá dúró nígbà tí ó bá ń gbọ́ ohùn rẹ̀.

5. Ọlọ́run fi ohùn rẹ̀ sán àrá níọ̀nà ìyanu; ohùn ńláńlá ni íṣe tí àwa kò le mọ̀.

6. Nítori tí ó wí fún Sínóó pé, Ìwọ rọ̀sílẹ̀ ayé, àti pẹ̀lú fún ọwọ́ òjò, àti fún òjò ńlá agbára rẹ̀.

7. Ó fi èdìdì di ọwọ́ gbogbo ènìyàn kígbogbo wọn kí ó lè mọ iṣẹ́ rẹ̀ó sì tún dá olúkúlùkù ẹ̀nìyàn dúró lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀

8. Nígbà náà ní àwọn ẹranko wọ inúihò lọ, wọn a sì wà ni ipò wọn.

9. Láti ìhà gúsù ni ìjì àjàyíká tí jádewá, àti òtútù láti inú afẹ́fẹ́ ti tú àwọ̀sánmọ̀ ká.

10. Nípa ẹ̀mí Ọlọ́run a fí ìdí-omi fúnni, ibú-omi á sì sún kì.

11. Pẹ̀lúpẹ̀lú ó fi omi púpọ̀ múàwọ̀sánmọ̀ wúwo, a sì túàwọ̀sánmọ̀ ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ká ara wọn.

12. Àwọn wọ̀nyí i káàriri nípà ìlànàrẹ̀, kí wọn kí ó lé ṣe ohunkohuntí ó pa láṣẹ fún wọn lórí ilẹ̀ ayé.

Ka pipe ipin Jóòbù 37