Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 33:7-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Kíyèsí i, ẹrù ń lá mi kì yóò bà ọ;bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi kì yóò wúwo sí ọ lára.

8. “Nítòótọ́ ìwọ sọ ní etí mi, èmí sìgbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé,

9. ‘Èmí mọ́, laini ẹ̀ṣẹ̀ ìrékọjá;Àláìṣẹ̀ ní èmí; bẹ́ẹ̀ àìṣéédéé kò sí ní ọwọ́ mi.

10. Kíyèsí i, Ọlọ́run ti rí àìṣedéédéépẹ̀lú mi; ó kà mí sì ọ̀tá rẹ̀.

11. Ó kàn ẹ̀ṣẹ̀ mi sínú àbà; o kíyèsiipa ọ̀nà mi gbogbo.’

12. “Kíyèsí i, nínú èyí ìwọ sìnà! Èmí odá ọ lóhùn pé, Ọlọ́run tóbi jù ènìyàn lọ!

13. Nítorí kí ni ìwọ ṣe ń báa jà, wí pé,òun kò níi sọ ọ̀rọ̀ kan nítorí iṣẹ́ rẹ̀?

Ka pipe ipin Jóòbù 33