Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 33:4-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ẹ̀mí Ọlọ́run Ní ó tí dá mi,Àti ìmísí Olódùmáre ni ó ti fún mi ní ìyè.

5. Bí ìwọ bá le dá mi lóhùn,tò ọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́ṣẹẹsẹ níwájú mi; dìdé!

6. Kíyèsí i, bí ìwọ ṣe jẹ́ ti Ọlọ́run,bẹ́ẹ̀ ni èmí náà; láti amọ̀ wá ni a sì ti dá mi pẹ̀lú

7. Kíyèsí i, ẹrù ń lá mi kì yóò bà ọ;bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi kì yóò wúwo sí ọ lára.

8. “Nítòótọ́ ìwọ sọ ní etí mi, èmí sìgbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé,

9. ‘Èmí mọ́, laini ẹ̀ṣẹ̀ ìrékọjá;Àláìṣẹ̀ ní èmí; bẹ́ẹ̀ àìṣéédéé kò sí ní ọwọ́ mi.

10. Kíyèsí i, Ọlọ́run ti rí àìṣedéédéépẹ̀lú mi; ó kà mí sì ọ̀tá rẹ̀.

11. Ó kàn ẹ̀ṣẹ̀ mi sínú àbà; o kíyèsiipa ọ̀nà mi gbogbo.’

Ka pipe ipin Jóòbù 33