27. Ó wá sọ́dọ̀ ènìyàn ó sì wí pé èmiṣẹ̀, kò sì sí èyí tí o tọ́, mo sì tiyí èyí tí ó tọ́ po, a kò sì san ẹ̀san rẹ̀ fún mi;
28. ó ti gba ọkàn mi kúrò nínú ìlọsínú ihò, ẹ̀mí mi yóò sì rí ìmọ́lẹ̀!
29. “Wò ó! Nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́runmáa ń ṣe fún ènìyàn nígbà méjì àti nígbà mẹ́ta,
30. Láti mú ọkàn rẹ padà kúrò nínúisà òkú, láti fi ìmọ́lẹ̀ alààyè mọ́ sí i.
31. “Jóòbù, kíyèsìí gidigidi kí o sì fetísí mi; pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì máa sọ ọ́
32. Bí ìwọ bá sì ní ohun íwí, dámi lóhùn; máa sọ, nítorí pé èmi fẹ́ dá ọ láre.
33. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, gbọ́ tèmi; pa ẹnu rẹmọ́ èmi ó sì kọ́ ọ ní ọgbọ́n.”