Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 33:25-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Ara rẹ̀ yóò sì di ọ̀tun bí i ti ọmọkékeré, yóò sì tún padà sí ọjọ́ ìgbà èwe rẹ̀;

26. Ó gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, òun sì seoju rere rẹ̀, o sì rí ojú rẹ̀ pẹ̀lúayọ̀, òhun o san òdodo rẹ̀ padà fún ènìyàn

27. Ó wá sọ́dọ̀ ènìyàn ó sì wí pé èmiṣẹ̀, kò sì sí èyí tí o tọ́, mo sì tiyí èyí tí ó tọ́ po, a kò sì san ẹ̀san rẹ̀ fún mi;

28. ó ti gba ọkàn mi kúrò nínú ìlọsínú ihò, ẹ̀mí mi yóò sì rí ìmọ́lẹ̀!

29. “Wò ó! Nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́runmáa ń ṣe fún ènìyàn nígbà méjì àti nígbà mẹ́ta,

30. Láti mú ọkàn rẹ padà kúrò nínúisà òkú, láti fi ìmọ́lẹ̀ alààyè mọ́ sí i.

31. “Jóòbù, kíyèsìí gidigidi kí o sì fetísí mi; pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì máa sọ ọ́

32. Bí ìwọ bá sì ní ohun íwí, dámi lóhùn; máa sọ, nítorí pé èmi fẹ́ dá ọ láre.

Ka pipe ipin Jóòbù 33