Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 33:18-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Ó sì fa ọkàn rẹ̀ pàdà kúro nínúìsà-òkú, àti ẹ̀mí rẹ̀ láti ṣẹ̀gbé lọ́wọ́ ìdà.

19. A sì nà á lórí ibùsùn ìrọra rẹ̀;Pẹ̀lúpẹ̀lú a fi ìjà egungun rẹ̀ ti ó dúró pẹ́ nà án.

20. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀mírẹ kọ ounjẹ, ọkàn rẹ̀ sì kọ oúnjẹ dídùn.

21. Ẹran ara rẹ̀ run, títí a kò sì fi lè ríi mọ́egungun rẹ̀ tí a kò rí sì ta jáde.

22. Àní ọkàn rẹ̀ sì súnmọ́ ìsà òkú,ẹ̀mí rẹ̀ sìsúnmọ́ ọ̀dọ̀ àwọn ìranṣẹ́ ikú.

23. “Bí oníṣẹ́ kan ba wà lọ́dọ̀ rẹ̀, ẹni tíń ṣe alágbàwí, ọ̀kan ninú ẹgbẹ̀rún láti fi ọ̀nà pípé hàn ni,

24. Nígbà náà ni ó ṣe oore ọ̀fẹ́ fún un ó sìwí pé, gbà á kúrò nínú ìlọ sínúìsà òkú èmi ti ràá pàdà;

25. Ara rẹ̀ yóò sì di ọ̀tun bí i ti ọmọkékeré, yóò sì tún padà sí ọjọ́ ìgbà èwe rẹ̀;

26. Ó gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, òun sì seoju rere rẹ̀, o sì rí ojú rẹ̀ pẹ̀lúayọ̀, òhun o san òdodo rẹ̀ padà fún ènìyàn

27. Ó wá sọ́dọ̀ ènìyàn ó sì wí pé èmiṣẹ̀, kò sì sí èyí tí o tọ́, mo sì tiyí èyí tí ó tọ́ po, a kò sì san ẹ̀san rẹ̀ fún mi;

28. ó ti gba ọkàn mi kúrò nínú ìlọsínú ihò, ẹ̀mí mi yóò sì rí ìmọ́lẹ̀!

29. “Wò ó! Nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́runmáa ń ṣe fún ènìyàn nígbà méjì àti nígbà mẹ́ta,

30. Láti mú ọkàn rẹ padà kúrò nínúisà òkú, láti fi ìmọ́lẹ̀ alààyè mọ́ sí i.

Ka pipe ipin Jóòbù 33