Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 33:13-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Nítorí kí ni ìwọ ṣe ń báa jà, wí pé,òun kò níi sọ ọ̀rọ̀ kan nítorí iṣẹ́ rẹ̀?

14. Nítorí pe Ọlọ́run sọ̀rọ̀ lẹ́ẹkan, ànílẹ́ẹkẹji, ṣùgbọn ènìyàn kò róye rẹ̀.

15. Nínú àlá, ní ojúran òru, nígbàtó orun ìjìká bá kùn ènìyàn lọ, ní sísùn lórí ìbùṣùn,

16. Nígbà náà ni ó lè sọ̀rọ̀ ní etíwọn, yóò sì dẹ́rùbà wọ́n pẹ̀lú ìbáwí,

17. Kí ó lè fa ènìyàn sẹ́yìn kúrò nínúètè rẹ̀; Kí ó sì pa ìgbéraga mọ́ kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn;

18. Ó sì fa ọkàn rẹ̀ pàdà kúro nínúìsà-òkú, àti ẹ̀mí rẹ̀ láti ṣẹ̀gbé lọ́wọ́ ìdà.

19. A sì nà á lórí ibùsùn ìrọra rẹ̀;Pẹ̀lúpẹ̀lú a fi ìjà egungun rẹ̀ ti ó dúró pẹ́ nà án.

20. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀mírẹ kọ ounjẹ, ọkàn rẹ̀ sì kọ oúnjẹ dídùn.

21. Ẹran ara rẹ̀ run, títí a kò sì fi lè ríi mọ́egungun rẹ̀ tí a kò rí sì ta jáde.

22. Àní ọkàn rẹ̀ sì súnmọ́ ìsà òkú,ẹ̀mí rẹ̀ sìsúnmọ́ ọ̀dọ̀ àwọn ìranṣẹ́ ikú.

Ka pipe ipin Jóòbù 33