Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 32:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Ènìyàn ńláńlá kì íṣe ọlọ́gbọ́n,Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbà ní òye ẹ̀tọ́ kò yé.

10. “Nítorí náà ní èmí ṣe wí pé: Ẹ dẹtí sílẹ̀ sí mi;èmí pẹ̀lú yóò fi ìmọ̀ mi hàn.

11. Kíyèsí i, èmí ti dúró de ọ̀rọ̀ yín;Èmi fetísí àròyé yín, nígbà tíẹ̀yin ń wá ọ̀rọ̀ ti ẹ̀nyín yóò sọ;

12. Àní mo fíyèsí yín tinútinú; sìkíyèsí i, kò sí ẹnìkan nínú yín tí ó le já Jóòbù ní irọ́, tàbí tí ó lèdá a lóhùn àríyànjiyàn rẹ̀!

13. Kí ẹ̀yín kí ó má ṣe wí pé, àwa wáọgbọ́n ní àwárí: Ọlọ́run ni ó lè bì í ṣubú, kì í ṣe ènìyàn.

Ka pipe ipin Jóòbù 32