Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 32:7-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Èmi wí pé ọjọjọ́ ni ìbá sọ̀rọ̀, àtiọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ní ìbá kọ́ ni ní ọgbọ́n.

8. Ṣùgbọ́n ẹ̀mi kan ní ó wà nínúènìyàn àti ìmísí Olódùmarè ní ì sì máa fún wọn ní òye.

9. Ènìyàn ńláńlá kì íṣe ọlọ́gbọ́n,Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbà ní òye ẹ̀tọ́ kò yé.

10. “Nítorí náà ní èmí ṣe wí pé: Ẹ dẹtí sílẹ̀ sí mi;èmí pẹ̀lú yóò fi ìmọ̀ mi hàn.

11. Kíyèsí i, èmí ti dúró de ọ̀rọ̀ yín;Èmi fetísí àròyé yín, nígbà tíẹ̀yin ń wá ọ̀rọ̀ ti ẹ̀nyín yóò sọ;

12. Àní mo fíyèsí yín tinútinú; sìkíyèsí i, kò sí ẹnìkan nínú yín tí ó le já Jóòbù ní irọ́, tàbí tí ó lèdá a lóhùn àríyànjiyàn rẹ̀!

13. Kí ẹ̀yín kí ó má ṣe wí pé, àwa wáọgbọ́n ní àwárí: Ọlọ́run ni ó lè bì í ṣubú, kì í ṣe ènìyàn.

14. Bí òun kò ti sọ̀rọ̀ sí mi, bẹ́ẹ̀ni èmí kì yóò fi ọ̀rọ̀ yín dá a lóhùn.

15. “Ẹnu sì yà wọ́n, wọn kò sì dáhùnmọ́, wọ́n síwọ́ ọ̀rọ̀ ísọ́.

16. Mo si reti, nítorí wọn kò sìfọhún, wọ́n dákẹ́ jẹ́ẹ́; wọn kò sì dáhùn mọ́.

17. Bẹ́ẹ̀ ni èmí ò sì dáhùn nípa tièmí, èmí pẹ̀lú yóò sì fi ìmọ̀ mi hàn.

Ka pipe ipin Jóòbù 32