Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 31:8-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Ǹjẹ́ kí èmi kí ó gbìn kí ẹlòmìírànkí ó sì mújẹ, àní kí a fa irú ọmọ mi tu.

9. “Bí àyà mi bá di fífà sípasẹ̀ obinrin kan,tàbí bí mo bá lọ í ba de ènìyàn ní ẹnu ọ̀nà ilé aládùúgbò mi,

10. Ṣùgbọ́n kí àyà mi kí ó lọ ọlọ fúnẹlòmíràn, kí àwọn ẹlòmíràn kí ó tẹ̀ ara wọn ní ara rẹ̀.

11. Nítorí pé yóò jẹ́ ohun ìtìjú àníẹ̀ṣẹ̀ tí a ó ṣe onídàájọ́ rẹ̀

12. Nítorí pé iná ní èyí tí ó jó dé ibiìparun, tí ìbá sì fa gbòǹgbòohun ìbísí mi gbogbo tu.

13. “Tí mo bá sì se àìka ọ̀ràn ìránṣẹ́kùnrinmi tàbí ìránṣẹ́bìnrin mi sí, nígbà tí wọ́n bá ń bá mi jà;

14. Kí ni èmi ó ha ṣe nígbà tí Ọlọ́runbá dìde? Nígbà tí ó bá sì ṣe ìbẹ̀wò, ohùn kí ni èmi ó dá?

15. Ẹni tí ó dá mi ní inú kọ́ ni ó dá a?Ẹnìkan náà kí ó mọ wá ní inú ìyá wa?

16. “Bí mo bá fa ọwọ́ sẹ́yìn fún ìfẹ́inú talákà, tàbí bí mo bá sì mú kí ojú opó di aláìríran,

17. Tàbí tí mo bá nìkan bu òkèlè mijẹ, tí aláìní baba kò jẹ nínú rẹ̀;

18. Nítorí pé láti ìgbà èwe mi wá nia ti tọ́ ọ dàgbà pẹ̀lú mi bí ẹnipé baba, èmi sì ń ṣe ìtọ́jú opó láti inú ìyá mi wá:

19. Bí èmi bá rí olùpọ́njú láìní aṣọ,tàbí talákà kan láìní ìbora;

Ka pipe ipin Jóòbù 31